Kronika Kinni 28:9-15 BM

9 “Ìwọ Solomoni, ọmọ mi, mọ Ọlọrun àwọn baba rẹ, kí o sì fi gbogbo ọkàn rẹ sìn ín tìfẹ́tìfẹ́, nítorí OLUWA a máa wádìí ọkàn, ó sì mọ gbogbo èrò ati ète eniyan. Bí o bá wá OLUWA, o óo rí i, ṣugbọn bí o bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo ta ọ́ nù títí lae.

10 Kíyèsára, nítorí pé OLUWA ti yàn ọ́ láti kọ́ ilé kan tí yóo jẹ́ ibi mímọ́, ṣe gírí, kí o sì kọ́ ọ.”

11 Dafidi bá fún Solomoni ní àwòrán tẹmpili náà tí wọ́n fi ọwọ́ yà, ati ti àwọn ilé mìíràn tí yóo kọ́ mọ́ tẹmpili, ati ti àwọn ilé ìṣúra rẹ̀, àwọn yàrá òkè, àwọn yàrá ti inú, ati ti yàrá ìtẹ́ àánú;

12 ati àwòrán gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe sinu àgbàlá ilé OLUWA, ati ti àwọn yàrá káàkiri, àwọn ilé ìṣúra tí yóo wà ninu ilé Ọlọrun, ati ti àwọn ilé ìṣúra tí wọ́n o máa kó ohun tí a yà sọ́tọ̀ fún OLUWA pamọ́ sí.

13 Dafidi tún fún un ní ìwé ètò pípín àwọn alufaa ati àwọn ọmọ Lefi sí ìsọ̀rí-ìsọ̀rí, ati ètò gbogbo iṣẹ́ ìsìn inú ilé OLUWA, ti àwọn ohun èlò fún ìsìn ninu ilé OLUWA;

14 àkọsílẹ̀ ìwọ̀n wúrà fún gbogbo ohun èlò wúrà fún ìsìn kọ̀ọ̀kan, ti ìwọ̀n fadaka fún gbogbo ohun èlò fadaka fún ìsìn kọ̀ọ̀kan,

15 ti ìwọ̀n àwọn ọ̀pá fìtílà wúrà ati àwọn fìtílà wọn, ti ìwọ̀n fadaka fún ọ̀pá fìtílà kan ati àwọn fìtílà wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlò olukuluku wọn ninu ìsìn.