2 Ó sì ní ìyàwó méjì: orúkọ wọn ni Hánà àti Pẹ̀nínà: Pẹ̀nínà ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hánà kò ní.
3 Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa alágbára jùlọ ní Ṣílò, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Élì méjèèjì, Hófínì àti Fínéhásì ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 Nígbàkígbà tí ó bá kan Elikánà láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Pẹ̀nínà àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hánà nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín in níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hánà bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín-in níràn títí tí yóò fi máa sunkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 Elikánà ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hánà èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”