1 Sámúẹ́lì 21:1-6 BMY

1 Dáfídì sì wá sí Nóbù sọ́dọ̀ Áhímélékì àlùfáà, Áhímélékì sì bẹ̀rù láti pàdé Dáfídì, ó sì wí fún un pé, “Èé ha ti rí tí o fi ṣe ìwọ nìkan, àti tí kò sì sí ọkùnrin kan tí ó pẹ̀lú rẹ.”

2 Dáfídì sì wí fún Áhímélékì àlùfáà pé, “Ọbá pàṣẹ iṣẹ́ kan fún mi, ó sì wí fún mi pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ìdí iṣẹ́ náà ti mo rán ọ, àti èyí tí èmi ti pàṣẹ fún ọ.’ Èmi sì yan àwọn ìránṣẹ́ mi sí ibí báyìí.

3 Ǹjẹ́ kín ni ó wà ní ọwọ́ rẹ̀? Fún mi ni ìṣù àkàrà márùn ún tabi ohunkohun tí o bá rí.”

4 Àlùfáà náà sí dá Dáfídì lóhùn ó sì wí pé, “Kò sí àkàrà mìíràn lọ́wọ́ mi bí kò ṣe àkàrà mímọ́; Kìkì pé bi àwọn ọmọkùnrin bá ti pá ara wọn mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin!”

5 Dáfídì sì dá àlùfáà náà lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Nítòótọ́ ni a tí ń pa ara wá mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin nígbàkùúgbà ti mo bá jáde ìrìn-àjò, gbogbo nǹkan àwọn ọmọkùnrin náà ni ó mọ́, pàápàá nígbà ìrìn-àjò kékèké; kò há ní mọ́ jù bẹ́ẹ̀ lọ lónìí bí?”

6 Bẹ́ẹ̀ ni àlùfáà náà sì fí àkàrà mímọ́ fún un; nítorí tí kò sí àkàrà mìíràn nibẹ̀ bí kò ṣe àkàrà ìfihàn tí a ti kó kúrò níwájú Olúwa, láti fi àkàrà gbígbóná síbẹ̀ ní ọjọ́ tí a kó o kúrò.