41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
42 Ábígáílì sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn iránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùnún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; oun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, o sì wá di aya rẹ̀.
43 Dáfídì sì mú Áhínóámù ará Jésírẹ́lì; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
44 Ṣùgbọ́n Ṣọ́ọ̀lù ti fi Míkálì ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dáfídì, fún Fátíélì ọmọ Láìsi tí i ṣe ara Gálímù.