Jẹnẹsisi 3:13-19 BM

13 OLUWA Ọlọrun bi obinrin náà pé, “Irú kí ni o dánwò yìí?” Obinrin náà dáhùn, ó ní, “Ejò ni ó tàn mí tí mo fi jẹ ẹ́.”

14 OLUWA Ọlọrun bá sọ fún ejò náà pé,“Nítorí ohun tí o ṣe yìí,o di ẹni ìfibú jùlọ láàrin gbogbo àwọn ẹran ọ̀sìn ati àwọn ẹranko.Àyà rẹ ni o óo máa fi wọ́ káàkiri,erùpẹ̀ ni o óo sì máa jẹ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

15 N óo dá ọ̀tá sí ààrin ìwọ ati obinrin náà,ati sí ààrin atọmọdọmọ rẹ ati atọmọdọmọ rẹ̀.Wọn óo máa fọ́ ọ lórí,ìwọ náà óo sì máa bù wọ́n ní gìgísẹ̀ jẹ.”

16 Lẹ́yìn náà Ọlọrun wí fún obinrin náà pé,“N óo fi kún ìnira rẹ nígbà tí o bá lóyún,ninu ìrora ni o óo máa bímọ.Sibẹsibẹ, lọ́dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóo máa fà sí,òun ni yóo sì máa ṣe olórí rẹ.”

17 Ó sọ fún Adamu, pé,“Nítorí pé o gba ohun tí aya rẹ wí fún ọ,o sì jẹ ninu èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé o kò gbọdọ̀ jẹ,mo fi ilẹ̀ gégùn-ún títí lae nítorí rẹ.Pẹlu ìnira ni o óo máa mú oúnjẹ jáde láti inú ilẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

18 Ẹ̀gún ati òṣùṣú ni ilẹ̀ yóo máa hù jáde fún ọ,ewéko ni o óo sì máa jẹ.

19 Iṣẹ́ àṣelàágùn ni o óo máa ṣe, kí o tó rí oúnjẹ jẹ,títí tí o óo fi pada sí ilẹ̀,nítorí inú rẹ̀ ni a ti mú ọ wá.Erùpẹ̀ ni ọ́,o óo sì pada di erùpẹ̀.”