Jẹnẹsisi 36 BM

Àwọn Ìran Esau

1 Àkọsílẹ̀ ìran Esau, tí àdàpè rẹ̀ ń jẹ́ Edomu nìyí:

2 Ninu àwọn ọmọbinrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ aya, ekinni ń jẹ́ Ada, ọmọ Eloni ará Hiti, ekeji ń jẹ́ Oholibama, ọmọ Ana tí baba rẹ̀ ń jẹ́ Sibeoni, ará Hifi.

3 Ẹkẹta ń jẹ́ Basemati ọmọ Iṣimaeli, arabinrin Nebaiotu.

4 Ada bí Elifasi fún Esau, Basemati bí Reueli.

5 Oholibama bí Jeuṣi, Jalamu ati Kora. Àwọn ni ọmọ Esau, tí àwọn aya rẹ̀ bí fún un ní ilẹ̀ Kenaani.

6 Nígbà tí ó ṣe, Esau kó àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ lọkunrin ati lobinrin, gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn mààlúù rẹ̀, àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ̀, ati gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ti kójọ ní ilẹ̀ Kenaani, ó kó kúrò ní ilẹ̀ Kenaani lọ́dọ̀ Jakọbu, arakunrin rẹ̀.

7 Ìdí ni pé ọrọ̀ wọn ti pọ̀ ju kí wọ́n jọ máa gbé pọ̀ lọ, ilẹ̀ tí wọ́n sì ti ń ṣe àtìpó kò gbà wọ́n mọ́, nítorí pé wọ́n ní ẹran ọ̀sìn tí ó pọ̀.

8 Bẹ́ẹ̀ ni Esau ṣe di ẹni tí ń gbé orí òkè Seiri. Esau kan náà ni ń jẹ́ Edomu.

9 Àkọsílẹ̀ ìran Esau, baba àwọn ará Edomu, tí ń gbé orí òkè Seiri nìyí:

10 orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ ni, Elifasi, tí Ada bí, ati Reueli, tí Basemati bí.

11 Àwọn ọmọ Elifasi ni: Temani, Omari, Sefo, Gatamu ati Kenasi.

12 (Elifasi, ọmọ Esau ní obinrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Timna, òun ni ó bí Amaleki fún un.) Àwọn ni àwọn ọmọ Ada, aya Esau.

13 Àwọn ọmọ Reueli ni Nahati, Sera, Ṣama, ati Misa. Àwọn ni àwọn ọmọ Basemati, aya Esau.

14 Àwọn ọmọ tí Oholibama, ọmọ Ana, ọmọ Sibeoni, aya Esau, bí fún un ni Jeuṣi, Jalamu ati Kora.

15 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ìjòyè ninu àwọn ọmọ Esau nìwọ̀nyí, Lára àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, tí Ada bí fún un: Temani, Omari, Sefo, Kenasi.

16 Kora, Gatamu, ati Amaleki. Àwọn wọnyii jẹ́ ọmọ Ada, aya Esau.

17 Lára àwọn ọmọ Reueli, ọmọ Esau, àwọn tí wọ́n jẹ́ ìjòyè ni: Nahati, Sera, Ṣama, ati Misa. Àwọn ni ìjòyè tí wọ́n ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Reueli, ní ilẹ̀ Edomu, wọ́n sì jẹ́ ọmọ Basemati, aya Esau.

18 Lára àwọn ọmọ Oholibama, aya Esau: àwọn tí wọ́n jẹ́ ìjòyè ni: Jeuṣi, Jalamu, ati Kora. Àwọn ni ìjòyè tí wọ́n ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Oholibama, ọmọ Ana, aya Esau.

19 Wọ́n jẹ́ ọmọ Esau, tí àdàpè rẹ̀ ń jẹ́ Edomu, àwọn sì ni ìjòyè tí wọ́n ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ṣẹ̀.

Àwọn Ìran Seiri

20 Àwọn ọmọ Seiri ará Hori, tí ń gbé ilẹ̀ náà nìyí: àwọn ọmọ rẹ̀ ni: Lotani, Ṣobali, Sibeoni ati Ana,

21 Diṣoni, Eseri, ati Diṣani, àwọn ni ìjòyè ní ilẹ̀ Hori, wọ́n sì jẹ́ ọmọ Seiri ní ilẹ̀ Edomu.

22 Àwọn ọmọ Lotani ni Hori, ati Hemani, Timna ni arabinrin Lotani.

23 Àwọn ọmọ Ṣobali ni Alfani, Manahati, Ebali, Ṣefo ati Onamu.

24 Àwọn ọmọ Sibeoni ni Aya ati Ana. Ana yìí ni ó rí àwọn ìsun omi gbígbóná láàrin aginjù, níbi tí ó ti ń tọ́jú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Sibeoni, baba rẹ̀.

25 Àwọn ọmọ Ana ni, Diṣoni ati Oholibama.

26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni Hemdani, Eṣibani, Itirani, ati Kerani.

27 Àwọn ọmọ Eseri ni: Bilihani, Saafani, ati Akani.

28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi ati Arani.

29 Àwọn ìjòyè tí wọ́n ṣẹ̀ lára Hori nìwọ̀nyí: Lotani, Ṣobali, Sibeoni,

30 Diṣoni, Eseri, ati Diṣani. Àwọn ìjòyè ilẹ̀ Hori, gẹ́gẹ́ bí olórí ìdílé ìdílé wọn ní ilẹ̀ Seiri.

Àwọn Ọba Edomu

31 Àwọn ọba tí wọ́n jẹ ní ilẹ̀ Edomu kí ó tó di pé ẹnikẹ́ni jọba ní ilẹ̀ Israẹli nìwọ̀nyí:

32 Bela, ọmọ Beori jọba ní Edomu, orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.

33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu, ọmọ Sera, ará Bosira gorí oyè.

34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu ti ilẹ̀ Temani, gorí oyè.

35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi, ọmọ Bedadi, tí ó ṣẹgun Midiani, ní ilẹ̀ Moabu gorí oyè, orúkọ ìlú tirẹ̀ ni Afiti.

36 Nígbà tí Hadadi kú, Samila ti Masireka gorí oyè.

37 Nígbà tí Samila kú, Ṣaulu ará Rehoboti lẹ́bàá odò Yufurate gorí oyè.

38 Nígbà tí Ṣaulu kú, Baali Hanani, ọmọ Akibori gorí oyè.

39 Nígbà tí Baali Hanani ọmọ Akibori kú, Hadadi gorí oyè, orúkọ ìlú tirẹ̀ ni Pau, orúkọ aya rẹ̀ ni Mehetabeli, ọmọ Matiredi, ọmọbinrin Mesahabu.

40 Orúkọ àwọn ìjòyè tí wọ́n ṣẹ̀ lára Esau nìwọ̀nyí, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn ati ìlú tí olukuluku ti jọba: Timna, Alfa, Jeteti,

41 Oholibama, Ela, Pinoni,

42 Kenasi, Temani, Mibisari,

43 Magidieli ati Iramu. Àwọn ni ìjòyè ní Edomu, gẹ́gẹ́ bí ìlú wọn ní ilẹ̀ ìní wọn, Esau tí àdàpè rẹ̀ ń jẹ́ Edomu sì ni baba àwọn ará Edomu.