1 Ogun bẹ́ sílẹ̀ láàrin àwọn ará Filistia ati àwọn ọmọ Israẹli. Àwọn ọmọ Israẹli sá fún àwọn ará Filistia, wọ́n sì pa ọpọlọpọ àwọn ọmọ Israẹli ní orí òkè Giliboa.
2 Ọwọ́ wọn tẹ Saulu ati àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n pa Jonatani, Abinadabu ati Malikiṣua.
3 Ogun gbóná janjan yí Saulu ká, àwọn tafàtafà rí i, wọ́n ta á lọ́fà, ó sì fara gbọgbẹ́,
4 Saulu ba sọ fún ọdọmọkunrin tí ń ru ihamọra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì gún mi pa, kí àwọn aláìkọlà ará Filistia má baà fi mi ṣẹ̀sín.” Ṣugbọn ẹni tí ń ru ihamọra rẹ̀ kọ̀, nítorí pe ẹ̀rù bà á; nítorí náà, Saulu fa idà ara rẹ̀ yọ, ó sì ṣubú lé e.