5 Nígbà tí ọdọmọkunrin náà rí i pé Saulu kú, òun náà ṣubú lé idà rẹ̀, ó sì kú.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu, àwọn ọmọ rẹ̀ mẹtẹẹta ati àwọn ará ilé rẹ̀ ṣe kú papọ̀.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí wọn ń gbé àfonífojì Jesireeli gbọ́ pé àwọn ọmọ ogun ti sá lọ, ati pé Saulu ati àwọn ọmọ rẹ̀ ti kú, wọ́n sá kúrò ní ìlú wọn, àwọn ará Filistia wá wọ́n sì ń gbé ibẹ̀.
8 Ní ọjọ́ keji, nígbà tí àwọn ará Filistia wá láti kó ìkógun, wọ́n rí òkú Saulu ati ti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹtẹẹta lórí Òkè Giliboa.
9 Wọ́n bọ́ ihamọra Saulu, wọ́n gé orí rẹ̀, wọ́n sì rán àwọn oníṣẹ́ káàkiri gbogbo ilẹ̀ Filistini láti ròyìn ayọ̀ náà fún àwọn oriṣa wọn ati àwọn eniyan wọn.
10 Wọ́n kó àwọn ihamọra rẹ̀ sinu tẹmpili oriṣa wọn, wọ́n sì kan orí Saulu mọ́ ara ògiri tẹmpili Dagoni, oriṣa wọn.
11 Nígbà tí àwọn ará Jabeṣi Gileadi gbọ́ bí àwọn ará Filistia ti ṣe Saulu,