1 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọ̀tí líleẹnikẹ́ni tí ó bá sìnà nìpaṣẹ̀ wọn kò gbọ́n.
2 Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún;ẹnikẹ́ni tí ó bá mú-un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjàṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹnítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
5 Ètè ọkàn ènìyàn dàbí, omi jínjìn;ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń wí oore wọn jáde,ṣùgbọ́nn kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòótọ́.
7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkùìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.