Òwe 4 BMY

Ọgbọ́n Ni Ó Ga Jùlọ

1 Tẹ́tí, Ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetí sílẹ̀ kí o sì ní òye sí i

2 Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooroNítorí náà má ṣe kọ ìkọ́ni mi sílẹ̀

3 Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí,mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kanṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi

4 Ó kọ́ mi ó sì wí pé“Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró,pa òfin mí mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.

5 Gba ọgbọ́n, gba òye,Má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹṣẹ̀ kúrò nínú rẹ̀

6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́,fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojú tó ọ.

7 Ọgbọ́n ni ó ga jù; Nítorí náà gba ọgbọ́n.Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye

8 Gbé e ga, yóò sì gbé ọ gadìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.

9 Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹyóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”

10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ,Ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.

11 Mo tọ́ ọ sọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́nmo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.

12 Nígbà tí o rìn, ìgbẹ́sẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́nígbà tí o bá sáré, iwọ kì yóò kọsẹ̀.

13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ;tọ́jú u rẹ̀ dáradára Nítorí òun ni ìyè rẹ.

14 Má ṣe gbé ẹṣẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburútàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.

15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀;yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ

16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi,wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú

17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búrurúwọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.

18 Ipa ọ̀nà Olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùntí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí

19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri;wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.

20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ;fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi

21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójúpa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ;

22 Nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọnàti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn

23 Ju gbogbo nǹkan tó kù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́Nítorí òun ni oríṣun ìyè,

24 mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ;sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìṣọkúṣọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.

25 Jẹ́ kí ojú ù rẹ máa wo iwájú,jẹ́ kí ìwo ojú ù rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sáá.

26 Kíyèsí ìrìn ẹṣẹ̀ rẹsì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan

27 má ṣe yà sọ́tùn-ún tàbí ṣósìpa ẹṣẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31