Òwe 25 BMY

Àwọn Òwe Mìíràn Ti Sólómónì

1 Wọ̀nyí ni àwọn òwé mìíràn tí Sólómónì pa, tí àwọn ọkùnrin Hẹsikáyà ọba Júdà dà kọ.

2 Ògo Olúwa ní láti fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́;láti rí ìdí ọ̀rọ̀ kan ni ògo àwọn ọba.

3 Bí ọ̀run ṣe ga tó tí ayé sì jìnbẹ́ẹ̀ ni ó ṣòro láti mọ èrò ọkàn ọba.

4 Mú ìdàrọ́ kúrò lára fàdákàohun èlò yóò sì jáde fún alágbẹ̀dẹ fàdákà

5 mú ènìyàn búburú kúrò níwájú ọbaa ó sì fìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ nípaṣẹ̀ òdodo.

6 Má ṣe gbé ara rẹ ga níwájú ọba,má sì ṣe jìjàdù ààyè láàrin àwọn ènìyàn pàtàkì

7 Ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síhìn ín”ju wí pé kí ó dójú tì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.

8 Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rímá ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìnbí aládùúgbò rẹ bá dójú tì ọ́?

9 Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,má ṣe tú àsírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,

10 àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójú tì ọ́orúkọ burúkú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.

11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹó dàbí èṣo wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.

12 Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradárani ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.

13 Bí títutù òjò yìnyín ní àsíkò ìkórèni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtọ́ sí àwọn tí ó rán anó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.

14 Bí ojú ṣíṣú àti afẹ́fẹ́ láì sí òjòni ènìyàn tí ń yangàn nípa ẹ̀bùn tí kò fún ni.

15 Nípa ṣùúrù a lè yí ọba lọ́kàn padàahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ rírọ̀ sí egungun.

16 Bí ìwọ bá rí oyin, jẹ ẹ́ ní ìwọ̀nbabí o bá jẹ ẹ́ jù, ìwọ yóò sì bì í.

17 Má ṣe máa lọ sí ilé aládùúgbò rẹ nígbà gbogbotàbí kí ó máa lọ ṣíbẹ̀ lálọ jù, yóò sì kórìíra rẹ.

18 Bí àdá, idà tàbí ọ̀kọ̀ tí ó múni ènìyàn tí ó jẹ́rìí èké lòdì sí aládùúgbò rẹ̀.

19 Bí eyín tí ó bàjẹ́ tàbí ẹṣẹ̀ tí ó rọni ìgbẹ́kẹ̀lé lórí aláìṣòótọ́ ní àsìkò ìdàámú.

20 Bí ẹni tí ó bọ́ra kalẹ̀ ní ọjọ́ tí òtútù mú,tàbí iyọ̀ tí a fi ra ojú egbò ọgbẹ́ tàbí bí ọtí kíkan tí a dà sórí sódàní ẹni tí ń kọ orin sí ọkàn tí ó bàjẹ́.

21 Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ;bí òrùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mú.

22 Nípa ṣíṣe báyìí, ìwọ yóò wa ẹ̀yín iná lé e lórí Olúwa yóò sì san ọẹ̀san rẹ̀ fún ọ.

23 Bí afẹ́fẹ́ gúṣù ti í mú òjò wá,bí ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn ṣe ń mú ojú ìbínú wá.

24 Ó sàn láti gbé ní ibi igun kan lórí òrùléju láti bá aya oníjà gbé ilé pọ̀.

25 Bí omi tútù sí ẹni tí òrùngbẹ ń gbẹni ìròyìn ayọ̀ láti ọ̀nà jíjìn.

26 Bí ìsun tí ó di àbàtà tàbí kanga tí omi rẹ̀ bàjẹ́ni olódodo tí ó fi àyè gba ènìyàn búburú.

27 Kò dára láti jẹ oyin àjẹjù,bẹ́ẹ̀ ni kò pọ́nni lé láti máa wá ọlá fún ara ẹni.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31