Òwe 12 BMY

1 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀,ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kórìíra ìbáwí jẹ́ aláìgbọ́n.

2 Ènìyàn rere gba ojú rere lọ́dọ̀ Olúwaṣùgbọ́n Olúwa kórìíra alárekérekè ènìyàn.

3 A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburúṣùgbọ́n a kò le è fa Olódodo tu.

4 Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀ṣùgbọ́n aya adójútini dàbí ìgbà tí inú egungun rẹ̀ jẹrà.

5 Ète àwọn Olódodo dáraṣùgbọ́n ìmúra ènìyàn búburú jẹ́ ẹ̀tàn.

6 Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ àwọn Olódodo gbà wọ́n là.

7 A sí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́;ṣùgbọ́n ilé Olódodo dúró ṣinṣin.

8 A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.

9 Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láì lóúnjẹ.

10 Ènìyàn rere ń ṣaájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílòÀmọ́ ìwà tó dára jù tí ènìyàn búburú lè hù, ibi ni.

11 Ẹni tí ó bá dáko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásánlàsàn kò gbọ́n.

12 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógún àwọn ènìyàn ìkàṣùgbọ́n gbòǹgbò Olódodo ń gbilẹ̀.

13 A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹsẹ̀ rẹ̀ṣùgbọ́n Olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdàámú.

14 Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rerebí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.

15 Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀ṣùgbọ́n Ọlọgbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.

16 Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀,ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.

17 Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí tòótọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ ríṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.

18 Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọgbọ́n ń mú ìwòsàn wá.

19 Ètè tí ń sòótọ́ yóò wà láéláéṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.

20 Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburúṣùgbọ̀n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.

21 Ibi kì í ṣubú lu Olódodo ráráṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.

22 Olúwa kóìríra ètè tí ń parọ́ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn Olóòótọ́.

23 Ènìyàn Olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.

24 Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jọbaṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí sínsìnrú.

25 Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodòṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.

26 Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn sìnà.

27 Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹṣùgbọ́n ẹni tí kì í ṣe ọ̀lẹ máa ń díwọ̀n ohun ìní rẹ̀.

28 Ní ọ̀nà àwọn Olódodo ni ìyè wàní ọ̀nà náà ni àìkú wà.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31