6 Ọgbẹ́ láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ṣe é gbẹ́kẹ̀léṣùgbọ́n ọ̀tá máa ń fẹnu-koni-lẹ́nu púpọ̀.
7 Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yóṣùgbọ́n òróòro gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.
8 Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.
9 Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkànbẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó Ṣàkóso.
10 Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdàámú dé bá ọó sàn kí o jẹ́ aládúúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà síni.
11 Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn minígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.
12 Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fara pamọ́ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí kàkàkí ó dúró ó tẹ̀ṣíwájú, ó sì jìyà rẹ̀.