25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ síi nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹtàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra,
26 nítorí Aṣẹ́wó yóò sọ ọ́ di àkàrà lásánlàsànẹ̀mí rẹ gan an sì ni alágbérè ń dọdẹ.
27 Ǹjẹ́ ènìyàn ha le è gbé iná lé orí itankí aṣọ rẹ̀ sì má jòó?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?Kí ẹṣẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láì jìyà.
30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalènítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 Ṣíbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méjebí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.