3 Nítorí náà, Dafidi pe gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sí Jerusalẹmu, kí wọ́n baà lè gbé Àpótí Majẹmu OLUWA wá sí ibi tí ó pèsè sílẹ̀ fún un.
4 Dafidi kó àwọn ọmọ Aaroni ati àwọn ọmọ Lefi jọ:
5 Iye àwọn ọmọ Lefi tí ó kó jọ láti inú ìdílé kọ̀ọ̀kan nìwọ̀nyí: láti inú ìdílé Kohati: ọgọfa (120) ọkunrin, Urieli ni olórí wọn;
6 láti inú ìdílé Merari: igba ó lé ogún (220) ọkunrin, Asaaya ni olórí wọn,
7 láti inú ìdílé Geriṣomu, aadoje (130) ọkunrin, Joẹli ni olórí wọn;
8 láti inú ìdílé Elisafani, igba (200) ọkunrin, Ṣemaaya ni olórí wọn,
9 láti inú ìdílé Heburoni, ọgọrin ọkunrin, Elieli ni olórí wọn,