Kronika Kinni 22:3-9 BM

3 Ó kó ọpọlọpọ irin jọ, tí wọn óo fi rọ ìṣó, tí wọn yóo fi kan àwọn ìlẹ̀kùn ati ìdè, ó kó idẹ jọ lọpọlọpọ pẹlu, ju ohun tí ẹnikẹ́ni lè wọ̀n lọ,

4 ati ọpọlọpọ igi kedari. Ó pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tí eniyan kò le kà wọ́n, nítorí pé ọpọlọpọ igi kedari ni àwọn ará Sidoni ati Tire kó wá fún Dafidi.

5 Nítorí pe Dafidi ní, “Tẹmpili tí a óo kọ́ fún OLUWA gbọdọ̀ dára tóbẹ́ẹ̀ tí òkìkí rẹ̀ yóo kàn ká gbogbo ayé; bẹ́ẹ̀ sì ni Solomoni, ọmọ mi, tí yóo kọ́ ilé náà kéré, kò sì tíì ní ìrírí pupọ. Nítorí náà, n óo tọ́jú àwọn ohun èlò sílẹ̀ fún un.” Dafidi bá tọ́jú àwọn nǹkan tí wọn yóo lò sílẹ̀ lọpọlọpọ kí ó tó kú.

6 Dafidi bá pe Solomoni, ọmọ rẹ̀, ó pàṣẹ fún un pé kí ó kọ́ ilé kan fún OLUWA Ọlọrun Israẹli.

7 Ó ní, “Ọmọ mi, mo ní i lọ́kàn láti kọ́ tẹmpili kan fún orúkọ OLUWA Ọlọrun mi,

8 ṣugbọn OLUWA sọ fún mi pé mo ti ta ọpọlọpọ ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, mo sì ti ja ọpọlọpọ ogun; nítorí ọpọlọpọ ìtàjẹ̀sílẹ̀ náà, òun kò ní gbà pé kí n kọ́ tẹmpili òun.

9 OLUWA ní n óo bí ọmọkunrin kan tí ìjọba rẹ̀ yóo jẹ́ ìjọba alaafia, ó ní òun óo fún un ní alaafia, gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ yíká kò sì ní yọ ọ́ lẹ́nu. Solomoni ni orúkọ rẹ̀ yóo máa jẹ́. Ní ìgbà tirẹ̀, Israẹli yóo wà ní alaafia ati àìléwu.