5 O si fi awọn onidajọ si ilẹ na, ninu gbogbo ilu olodi Juda, lati ilu de ilu,
6 O si wi fun awọn onidajọ pe, Ẹ kiyesi ohun ti ẹnyin nṣe! nitori ti ẹnyin kò dajọ fun enia bikòṣe fun Oluwa, ti o wà pẹlu nyin ninu ọ̀ran idajọ.
7 Njẹ nisisiyi, jẹ ki ẹ̀ru Oluwa ki o wà lara nyin, ẹ ma ṣọra, ki ẹ si ṣe e; nitoriti kò si aiṣedede kan lọdọ Oluwa Ọlọrun wa, tabi ojuṣaju enia, tabi gbigba abẹtẹlẹ.
8 Pẹlupẹlu ni Jerusalemu, Jehoṣafati yàn ninu awọn ọmọ Lefi, ati ninu awọn alufa, ati ninu awọn olori awọn baba Israeli, fun idajọ Oluwa, ati fun ẹjọ; nwọn si ngbe Jerusalemu.
9 O si kilọ fun wọn, wipe, Bayi ni ki ẹnyin ki o mã ṣe, ni ibẹ̀ru Oluwa, li otitọ, ati pẹlu ọkàn pipé.
10 Ẹjọ ki ẹjọ ti o ba si de ọdọ nyin lati ọdọ awọn arakunrin nyin ti ngbe ilu wọn, lãrin ẹ̀jẹ on ẹ̀jẹ, lãrin ofin pẹlu aṣẹ, ìlana ati ẹtọ́, ki ẹnyin ki o kilọ fun wọn, ki nwọn ki o máṣe dẹṣẹ si Oluwa, ibinu a si wá sori nyin, ati sori awọn arakunrin nyin: ẹ ṣe bẹ̃ gẹgẹ, ẹnyin kì yio si jẹbi.
11 Si wõ, Amariah, alufa ni olori lori nyin ni gbogbo ọ̀ran Oluwa; ati Sebadiah, ọmọ Iṣmaeli, alakoso ile Juda, fun ọ̀ran ọba; pẹlupẹlu ẹnyin ni olutọju awọn ọmọ Lefi pẹlu nyin. Ẹ mu ara le, ki ẹ si ṣe, Oluwa yio pẹlu ẹni-rere.