1 Náhásì ará Ámónì gòkè lọ, ó sì dó ti Jabesi-Gílíádì, gbogbo ọkùnrin Jábésì sì wí fún Néhásì pé, “Bá wa ṣe ìpinnú, àwa yóò sì máa sìn ọ́.”
2 Ṣùgbọ́n Náhásì ará Ámónì sì wí fún un pé, “Nípa èyí ni èmi ó ò fi bá a yín ṣe ìpinnu, nípa yíyọ gbogbo ojú ọtún yín kúró, èmi o si fi yín se ẹlẹ́yà lójú gbogbo Ísírẹ́lì.”
3 Àwọn àgbà Jábésì sì wí fún un pé, “Fún wa ní ọjọ́ méje kí àwa lè rán oníṣẹ́ sí gbogbo Ísírẹ́lì; àti agbègbè bí ẹni kankan kò bá sì jáde láti gbà wá, àwa yóò fi ara wa fún ọ.”
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà sì wá sí Gíbíà tí ó jẹ́ ìlú Ṣọ́ọ̀lù, wọ́n sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, gbogbo wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sunkún.