2. Kro 25:4-10 YCE

4 Ṣugbọn kò pa awọn ọmọ wọn, ṣugbọn o ṣe gẹgẹ bi a ti kọ ọ ninu ofin ninu iwe Mose, ti Oluwa ti paṣẹ wipe, Awọn baba kì yio kú fun awọn ọmọ, bẹ̃li awọn ọmọ kì yio kú fun awọn baba, ṣugbọn olukuluku ni yio kú nitori ẹ̀ṣẹ rẹ̀.

5 Amasiah si kó Juda jọ, o si tò wọn lẹsẹsẹ gẹgẹ bi ile baba wọn, awọn balogun ẹgbẹgbẹrun ati balogun ọrọrun, ani gbogbo Juda ati Benjamini, o si ka iye wọn lati ẹni ogun ọdun ati jù bẹ̀ lọ, o si ri wọn li ọkẹ mẹdogun enia ti a yàn, ti o le jade lọ si ogun, ti o si le lo ọ̀kọ ati asà.

6 O si bẹ̀ ọkẹ marun ogun alagbara akọni ọkunrin lati inu Israeli wá fun ọgọrun talenti fadakà.

7 Ṣugbọn enia Ọlọrun kan tọ̀ ọ wá, wipe, Ọba, máṣe jẹ ki ogun Israeli ki o ba ọ lọ: nitoriti Oluwa kò wà pẹlu Israeli, ani gbogbo awọn ọmọ Efraimu.

8 Ṣugbọn bi iwọ o ba lọ, ma lọ, mu ara le fun ogun na: Ọlọrun yio bì ọ ṣubu niwaju ọta: Ọlọrun sa li agbara lati ṣe iranlọwọ, ati lati bì ni ṣubu.

9 Amasiah si wi fun enia Ọlọrun na pe, Ṣugbọn kili awa o ha ṣe nitori ọgọrun talenti ti mo ti fi fun ẹgbẹ-ogun Israeli? Enia Ọlọrun na si dahùn pe, O wà li ọwọ Oluwa lati fun ọ li ọ̀pọlọpọ jù eyi lọ.

10 Nigbana li Amasiah yà wọn, ani ẹgbẹ-ogun ti o ti tọ̀ ọ lati Efraimu wá, lati tun pada lọ ile wọn: ibinu wọn si ru gidigidi si Juda, nwọn si pada si ile wọn ni irunu.