1 Sámúẹ́lì 11:2-8 BMY

2 Ṣùgbọ́n Náhásì ará Ámónì sì wí fún un pé, “Nípa èyí ni èmi ó ò fi bá a yín ṣe ìpinnu, nípa yíyọ gbogbo ojú ọtún yín kúró, èmi o si fi yín se ẹlẹ́yà lójú gbogbo Ísírẹ́lì.”

3 Àwọn àgbà Jábésì sì wí fún un pé, “Fún wa ní ọjọ́ méje kí àwa lè rán oníṣẹ́ sí gbogbo Ísírẹ́lì; àti agbègbè bí ẹni kankan kò bá sì jáde láti gbà wá, àwa yóò fi ara wa fún ọ.”

4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà sì wá sí Gíbíà tí ó jẹ́ ìlú Ṣọ́ọ̀lù, wọ́n sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, gbogbo wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sunkún.

5 Nígbà náà gan an ni Ṣọ́ọ̀lù padà wá láti pápá, pẹ̀lú màlúù rẹ̀, ó sì béèrè pé, “kín ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn? Èéṣe tí wọ́n fi ń sunkún?” Nígbà náà ni wọ́n tún sọ fún wọn ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Jábésì.

6 Nígbà tí Ṣọ́ọ̀lù sì gbọ́ ọ̀rọ̀ wọn, ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà lé e pẹ̀lú agbára, inú rẹ̀ sì ru sókè.

7 Ó sì mú màlúù méjì, ó gé wọn sí wẹ́wẹ́, ó sì rán ẹyọyọ sí gbogbo Ísírẹ́lì nípa ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ náà, ó ní i ẹ kéde pé, “Èyí ni a ó ṣe sí màlúù ẹnikẹ́ni tí kò bá tọ Ṣọ́ọ̀lù àti Sámúẹ́lì lẹ́yìn.” Nígbà náà ni ìbẹ̀rù Olúwa sì mú àwọn ènìyàn, wọ́n sì jáde bí ènìyàn kan ṣoṣo.

8 Nígbà tí Ṣọ́ọ̀lù sì kó wọn jọ ní Bésékì, àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì tí a kà jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀dógún. (300,000) àwọn ọkùnrin Júdà sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀dógún (30,000).