2 “Láìsí àní àní,ẹ̀yin ni agbẹnusọ gbogbo eniyan,bí ẹ bá jáde láyé,ọgbọ́n kan kò tún ní sí láyé mọ́.
3 Bí ẹ ti ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà ní,ẹ kò sàn jù mí lọ.Ta ni kò mọ irú nǹkan, tí ẹ̀ ń sọ yìí?
4 Mo wá di ẹlẹ́yà lójú àwọn ọ̀rẹ́ mi,èmi tí mò ń ké pe Ọlọrun,tí ó sì ń dá mi lóhùn;èmi tí mo jẹ́ olódodo ati aláìlẹ́bi,mo wá di ẹlẹ́yà.
5 Lójú ẹni tí ara tù,ìṣòro kì í báni láìnídìí.Lójú rẹ̀, ẹni tí ó bá ṣìṣe ni ìṣòro wà fún.
6 Àwọn olè ń gbé ilé wọn ní alaafia,àwọn tí wọn ń mú Ọlọrun bínú wà ní àìléwu,àwọn tí ó jẹ́ pé agbára wọn ni Ọlọrun wọn.
7 “Ṣugbọn, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ẹranko, wọn óo sì kọ́ ọ,bi àwọn ẹyẹ, wọn yóo sì sọ fún ọ;
8 tabi kí o bi àwọn koríko, wọn yóo sì kọ́ ọ,àwọn ẹja inú òkun yóo sì ṣe àlàyé fún ọ.