Jobu 37 BM

1 “Nígbà tí mo gbọ́, ọkàn mi wárìrì,ó sì fò sókè ní ipò rẹ̀.

2 Gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ń dún bí ààrá,ati ariwo tí ń ti ẹnu rẹ̀ jáde.

3 Ó rán mànàmáná rẹ̀ sí wọn jákèjádò ojú ọ̀run,títí dé òpin ilẹ̀ ayé.

4 Lẹ́yìn náà, a gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,ó sọ̀rọ̀ ninu ọlá ńlá rẹ̀,bí ìgbà tí ààrá bá sán,sibẹsibẹ kò dá mànàmáná dúróbí àwọn eniyan ti ń gbóhùn rẹ̀.

5 Ohùn Ọlọrun dún bí ààrá tìyanu-tìyanu,a kò lè rí ìdí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.

6 Ó pàṣẹ pé kí yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀,bẹ́ẹ̀ náà ni òjò wẹliwẹli,ati ọ̀wààrà òjò.

7 Ó ká gbogbo eniyan lọ́wọ́ iṣẹ́ kò,kí wọ́n lè mọ iṣẹ́ rẹ̀.

8 Àwọn ẹranko wọ ihò wọn lọ,wọ́n dákẹ́ sibẹ, wọ́n sá pamọ́.

9 Ìjì líle fẹ́ jáde láti inú yàrá rẹ̀,òtútù sì mú wá láti inú afẹ́fẹ́ tí ń fẹ́.

10 Yìnyín ti inú èémí Ọlọrun wá,gbogbo omi inú odò sì dì.

11 Ó fi omi kún inú ìkùukùu,ìkùukùu sì fọ́n mànàmáná rẹ̀ ká.

12 Wọ́n ń yípo lábẹ́ ìtọ́ni rẹ̀,láti mú gbogbo àṣẹ tí ó pa ṣẹ, lórí ilẹ̀ alààyè.

13 Ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi ṣẹlẹ̀,bóyá fún àtúnṣe ni, tabi nítorí ilẹ̀ rẹ̀,tabi láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14 “Fetí sílẹ̀, ìwọ Jobu,dúró kí o sì ronú nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu Ọlọrun.

15 Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọrun ṣe pàṣẹ,tí ó sì mú kí mànàmáná awọsanma tàn?

16 Ǹjẹ́ o mọ̀ bí ó ṣe so awọsanma rọ̀,iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ ni;

17 ìwọ tí ooru mú nígbà tí ayé dákẹ́ rọ́rọ́nítorí pé afẹ́fẹ́ ìhà gúsù kò fẹ́?

18 Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ,kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán?

19 Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ,a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀,nítorí àìmọ̀kan wa.

20 Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni?Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì?

21 “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀runnígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma,nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ.

22 Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ,ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ.

23 Àwámárìídìí ni Olodumare–agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀.

24 Nítorí náà, gbogbo eniyan bẹ̀rù rẹ̀,kò sì náání àwọn tí wọ́n gbọ́n lójú ara wọn.”