Jobu 11 BM

1 Sofari ará Naama dáhùn pé,

2 “Ǹjẹ́ ó dára kí eniyan sọ ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ kalẹ̀ báyìí kí ó má sì ìdáhùn?Àbí, ṣé ọ̀pọ̀ ọ̀rọ̀ lè mú kí á dá eniyan láre?

3 Ṣé o rò pé ìsọkúsọ rẹ lè pa eniyan lẹ́nu mọ́ ni?Tabi pé bí o bá ń ṣe ẹlẹ́yà ẹnikẹ́ni kò lè dójútì ọ́?

4 Nítorí o sọ pé ẹ̀kọ́ rẹ tọ̀nà,ati pé ẹni mímọ́ ni ọ́ lójú Ọlọrun.

5 Ọlọrun ìbá ya ẹnu rẹ̀,kí ó sọ̀rọ̀ sí ọ.

6 Kì bá jẹ́ fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́,nítorí ìmọ̀ rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ.Mọ̀ dájú pé ìyà tí Ọlọrun fi jẹ ọ́kò to nǹkan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.

7 “Ǹjẹ́ o lè wádìí àwọn ohun ìjìnlẹ̀ nípa Ọlọrun?Tabi kí o tọpinpin Olodumare?

8 Ó ga ju ọ̀run lọ, kí lo lè ṣe sí i?Ó jìn ju isà òkú lọ, kí lo lè mọ̀ nípa rẹ̀?

9 Ó gùn ju ayé lọ,Ó sì fẹ̀ ju òkun lọ.

10 Tí ó bá ń kọjá lọ, tí ó sì ti eniyan mọ́lé,tí ó pe olúwarẹ̀ lẹ́jọ́,ta ló lè yẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ wò?

11 Nítorí ó mọ àwọn eniyan lásán,ṣé bí ó bá rí ẹ̀ṣẹ̀,kí ó má ṣe akiyesi rẹ̀?

12 Ó di ìgbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ bá bí ọmọ rẹ̀ ní eniyan,kí òmùgọ̀ eniyan tó gbọ́n.

13 “Bí o bá fi ọkàn rẹ sí ohun tí ó tọ́,o óo lè nawọ́ sí i.

14 Bí o bá ń dẹ́ṣẹ̀, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́,má sì ṣe jẹ́ kí ìwà burúkú, wà ní ọwọ́ rẹ.

15 Nígbà náà ni o óo tó lè fi ìgboyà gbójú sókè láìlẹ́bi;o óo wà láìléwu,o kò sì ní bẹ̀rù.

16 O óo gbàgbé àwọn ìyọnu rẹ,nígbà tí o bá sì ranti rẹ̀,yóo dàbí ìkún omi tí ó ti wọ́ lọ.

17 Ayé rẹ yóo mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ;òkùnkùn rẹ yóo sì dàbí òwúrọ̀.

18 Ọkàn rẹ óo balẹ̀, nítorí pé o ní ìrètí,a óo dáàbò bò ọ́, o óo sì sinmi láìséwu.

19 O óo sùn, láìsí ìdágìrì,ọpọlọpọ eniyan ni wọn óo sì máa wá ojurere rẹ.

20 Àwọn ẹni ibi óo pòfo;gbogbo ọ̀nà tí wọ́n lè gbà sá àsálàni yóo parẹ́ mọ́ wọn lójú,ikú ni yóo sì jẹ́ ìrètí wọn.”