4 Ta ló lè mú ohun mímọ́ jádeláti inú ohun tí kò mọ́?Kò sí ẹni náà.
5 Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá ọjọ́ fún un,tí o mọ iye oṣù rẹ̀,tí o sì ti pa ààlà tí kò lè rékọjá.
6 Mú ojú rẹ kúrò lára rẹ̀, kí ó lè sinmi,kí ó sì lè gbádùn ọjọ́ ayé rẹ̀ bí alágbàṣe.
7 “Nítorí pé ìrètí ń bẹ fún igi tí wọn gé,yóo tún pada rúwé,ẹ̀ka rẹ̀ kò sì ní ṣe aláìsọ.
8 Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ògbólógbòó ninu ilẹ̀,tí kùkùté rẹ̀ sì kú,
9 bí ó bá ti gbóòórùn omi, yóo sọ,yóo sì yọ ẹ̀ka bí ọ̀dọ́ irúgbìn.
10 Ṣugbọn bí eniyan bá kú, a óo tẹ́ ẹ sinu ibojì,bí ó bá ti gbẹ́mìí mì, ó di aláìsí.