1 Jobu bá dáhùn pé,
2 “Èmi náà ti gbọ́ irú nǹkan wọnyi rí,ọlọ́rọ̀ ìtùnú kòbákùngbé ni gbogbo yín.
3 Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ asán tí ẹ̀ ń sọ yìí tilẹ̀ lópin?Àbí, kí ní ń fa gbogbo àríyànjiyàn yìí?
4 Bí ẹ bá wà ní ipò mi,èmi náà lè sọ̀rọ̀ bí ẹ tí ń sọ̀rọ̀ yìí,kí n da ọ̀rọ̀ bò yín,kí n sì máa mi orí si yín.