4 Bí ẹ bá wà ní ipò mi,èmi náà lè sọ̀rọ̀ bí ẹ tí ń sọ̀rọ̀ yìí,kí n da ọ̀rọ̀ bò yín,kí n sì máa mi orí si yín.
5 Mo lè fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi fun yín lókun,kí ọ̀rọ̀ ìtùnú mi sì mú kí ara tù yín.
6 “Bí mo sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ kò mú kí ara tù mí,bí mo bá sì dákẹ́, ṣé dídákẹ́ lè tán ìrora mi?
7 Dájúdájú Ọlọrun ti dá mi lágara,ó ti sọ gbogbo ilé mi di ahoro.
8 Híhunjọ tí ara mi hunjọ, jẹ́ ẹ̀rí láti ta kò mí;rírù tí mo rù ta àbùkù mi,ó sì hàn lójú mi.
9 Ó ti fi ibinu fà mí ya,ó sì kórìíra mi;ó pa eyín keke sí mi;ọ̀tá mi sì ń fojú burúkú wò mí.
10 Àwọn eniyan ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà,wọ́n ń gbá mi létí,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi.