9 Ó ti fi ibinu fà mí ya,ó sì kórìíra mi;ó pa eyín keke sí mi;ọ̀tá mi sì ń fojú burúkú wò mí.
10 Àwọn eniyan ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà,wọ́n ń gbá mi létí,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi.
11 Ọlọrun fà mí lé eniyan burúkú lọ́wọ́,ó mú kí n ṣubú sí ọwọ́ àwọn ìkà.
12 Nígbà tí ó dára fún mi,ó fi ẹ̀yìn mi wọ́nlẹ̀,ó fún mi lọ́rùn, ó gbé mi ṣánlẹ̀,ó sì gbọ̀n mí yẹ́bẹ́yẹ́bẹ́;ó yàn mí sọjú bí àmì ìtafà sí.
13 Àwọn tafàtafà rẹ̀ yí mi ká,ó la kíndìnrín mi láìṣàánú mi,ó sì tú òróòro mi jáde.
14 Ó ń gbógun tì mí nígbà gbogbo,ó pakuuru sí mi bí ọmọ ogun.
15 “Mo fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara,mo sùn gbalaja sinu erùpẹ̀.