19 Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn,àwọn aláìlẹ́bi fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,
20 wọ́n ń wí pé, ‘Dájúdájú, àwọn ọ̀tá wa ti parun,iná sì ti jó gbogbo ohun tí wọ́n fi sílẹ̀.’
21 “Nisinsinyii gba ti Ọlọrun,kí o sì wà ní alaafia;kí ó lè dára fún ọ.
22 Gba ìtọ́ni rẹ̀,kí o sì kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ lékàn.
23 Bí o bá yipada sí Olodumare, tí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀,tí o bá mú ìwà aiṣododo kúrò ní ibùgbé rẹ,
24 bí o bá ri wúrà mọ́ inú erùpẹ̀,tí o fi wúrà Ofiri sí ààrin àwọn òkúta ìsàlẹ̀ odò,
25 bí Olodumare bá sì jẹ́ wúrà rẹ,ati fadaka olówó iyebíye rẹ,