1 Nígbà náà ni Jobu dáhùn pé,
2 “Lónìí, ìráhùn mi tún kún fún ẹ̀dùn,ọwọ́ Ọlọrun ń le lára mi,bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mò ń kérora.
3 Áà! Ìbá jẹ́ pé mo mọ ibi tí mo ti lè rí i ni,ǹ bá lọ siwaju ìtẹ́ rẹ̀!
4 Ǹ bá ro ẹjọ́ mi níwájú rẹ̀,gbogbo ẹnu ni ǹ bá fi ṣàròyé.
5 Ǹ bá gbọ́ èsì tí yóo fún mi,ati ọ̀rọ̀ tí yóo sọ fún mi.
6 Ṣé yóo gbéjà kò mí pẹlu agbára ńlá rẹ̀?Rárá o, yóo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
7 Ibẹ̀ ni olódodo yóo ti lè sọ ti ẹnu rẹ̀,yóo sì dá mi sílẹ̀ títí lae.