13 “Ṣugbọn Ọlọrun kìí yipada,kò sí ẹni tí ó lè yí i lọ́kàn pada.Ohun tí ó bá fẹ́ gan-an ni yóo ṣe.
14 Yóo ṣe ohun tí ó ti pinnu láti ṣe fún mi ní àṣeyọrí,ati ọpọlọpọ nǹkan bẹ́ẹ̀ yòókùtí ó tún ní lọ́kàn láti ṣe fún mi.
15 Ìdí nìyí tí ẹ̀rù fi bà mí níwájú rẹ̀,tí mo bá ro nǹkan wọnyi, jìnnìjìnnì rẹ̀ a bò mí.
16 Ọlọrun ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi,Olodumare ti dẹ́rùbà mí.
17 Nítorí pé òkùnkùn yí mi ká,òkùnkùn biribiri sì ṣú bò mí lójú.