8 “Wò ó! Mo lọ siwaju, kò sí níbẹ̀,mo pada sẹ́yìn, n kò gbúròó rẹ̀.
9 Mo wo apá ọ̀tún, n kò rí i,mo wo apá òsì, kò sí níbẹ̀.
10 Ṣugbọn ó mọ gbogbo ọ̀nà mi,ìgbà tí ó bá dán mi wò tán,n óo yege bíi wúrà.
11 Mò ń tẹ̀lé e lẹ́yìn, mo súnmọ́ ọn pẹ́kípẹ́kí,n kò tíì yipada kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
12 N kò tíì yapa kúrò ninu àṣẹ tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde,mò ń pa wọ́n mọ́ ninu ọkàn mi.
13 “Ṣugbọn Ọlọrun kìí yipada,kò sí ẹni tí ó lè yí i lọ́kàn pada.Ohun tí ó bá fẹ́ gan-an ni yóo ṣe.
14 Yóo ṣe ohun tí ó ti pinnu láti ṣe fún mi ní àṣeyọrí,ati ọpọlọpọ nǹkan bẹ́ẹ̀ yòókùtí ó tún ní lọ́kàn láti ṣe fún mi.