10 Àwọn aláìní ń rìn kiri ní ìhòòhò láìrí aṣọ wọ̀;ebi ń pa wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtí ọkà ni wọ́n rù.
11 Wọ́n ń fún òróró lára èso olifi tí ó wà ní oko ìkà,òùngbẹ sì ń gbẹ wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọtí ni wọ́n ń pọn.
12 Àwọn tí wọn ń kú lọ ń kérora ní ìgboro,àwọn tí a pa lára ń ké fún ìrànlọ́wọ́,ṣugbọn Ọlọrun kò fetísí adura wọn.
13 “A rí àwọn tí wọ́n kọ ìmọ́lẹ̀,tí wọn kò mọ ọ̀nà rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró ní ọ̀nà náà.
14 Bí ilẹ̀ bá ṣú, apànìyàn á dìde,kí ó lè pa talaka ati aláìní,a sì dàbí olè ní òru.
15 Alágbèrè pàápàá ń ṣọ́ kí ilẹ̀ ṣú,ó ń wí pé, ‘Kò sí ẹni tí yóo rí mi’;ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
16 Lóru, wọn á máa lọ fọ́ ilé kiri,ṣugbọn bí ilẹ̀ bá ti mọ́,wọn á ti ìlẹ̀kùn mọ́rí,wọn kì í rí ìmọ́lẹ̀.