1 Jobu bá dáhùn pé,
2 “Ìrànlọ́wọ́ wo ni ẹ ti ṣe fún àwọn tí wọn kò lágbára?Aláìlera wo ni ẹ ti gbàlà?
3 Ìmọ̀ràn wo ni ẹ ti fún àwọn aláìgbọ́n?Irú òye wo ni ẹ fihàn wọ́n?
4 Ta ló ń kọ yín ni ohun tí ẹ̀ ń sọ wọnyi?Irú ẹ̀mí wo sì ní ń gba ẹnu yín sọ̀rọ̀?
5 “Àwọn òkú wárìrì nísàlẹ̀.Omi ati àwọn olùgbé inú rẹ̀ pẹlu ń gbọ̀n rìrì.