15 Wúrà iyebíye kò lè rà á,fadaka kò sì ṣe é díwọ̀n iye rẹ̀.
16 A kò lè fi wúrà Ofiri díwọ̀n iye rẹ̀,tabi òkúta onikisi tabi safire tí wọ́n jẹ́ òkúta olówó iyebíye.
17 Ọgbọ́n níye lórí ju wúrà ati dígí lọ,a kò lè fi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà dáradára ṣe dípò rẹ̀.
18 Kí á má tilẹ̀ sọ ti iyùn tabi Kristali,ọgbọ́n ní iye lórí ju òkúta Pali lọ.
19 A kò lè fi wé òkúta topasi láti ilẹ̀ Etiopia,tabi kí á fi ojúlówó wúrà rà á.
20 “Níbo ni ọgbọ́n ti ń wá;níbo sì ni ìmọ̀ wà?
21 Ó pamọ́ lójú gbogbo ẹ̀dá alààyè,ati lójú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run.