5 Ní ti ilẹ̀, inú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde,ṣugbọn lábẹ́ rẹ̀, ó dàbí ẹnipé iná ń yí i po,ó gbóná janjan.
6 Safire ń bẹ ninu àwọn òkúta rẹ̀,wúrà sì ni erùpẹ̀ rẹ̀.
7 Ẹyẹ àṣá kò mọ ipa ọ̀nà ibẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ojú gúnnugún kò tó o.
8 Àwọn ẹranko onigbeeraga kò tíì tẹ ojú ọ̀nà náà,kinniun kò sì tíì gba ibẹ̀ kọjá rí.
9 “Eniyan á dá ọwọ́ rẹ̀ lé òkúta akọ, á gbẹ́ ẹ,á sì hú òkè ńlá tìdítìdí.
10 Á gbẹ́ ihò sinu àpáta,ojú rẹ̀ a sì tó àwọn ìṣúra iyebíye.
11 Á dí orísun àwọn odò,tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò fi lè sun,á sì wá àwọn ohun tí ó pamọ́ jáde.