9 “Eniyan á dá ọwọ́ rẹ̀ lé òkúta akọ, á gbẹ́ ẹ,á sì hú òkè ńlá tìdítìdí.
10 Á gbẹ́ ihò sinu àpáta,ojú rẹ̀ a sì tó àwọn ìṣúra iyebíye.
11 Á dí orísun àwọn odò,tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò fi lè sun,á sì wá àwọn ohun tí ó pamọ́ jáde.
12 Ṣugbọn níbo ni a ti lè rí ọgbọ́n?Níbo sì ni ìmọ̀ wà?
13 “Ẹnikẹ́ni kò mọ ọ̀nà ibi tí ó wà;bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ilẹ̀ alààyè.
14 Ibú sọ pé, ‘Kò sí ninu mi,’òkun sì ní, ‘Kò sí lọ́dọ̀ mi.’
15 Wúrà iyebíye kò lè rà á,fadaka kò sì ṣe é díwọ̀n iye rẹ̀.