15 Mo jẹ́ ojú fún afọ́jú,ati ẹsẹ̀ fún arọ.
16 Mo jẹ́ baba fún talaka,mo gba ẹjọ́ àlejò rò.
17 Mo ṣẹ́ ẹni ibi lápá,mo gba ẹni tí ó mú sílẹ̀.
18 “Nígbà náà, mo rò pé, n óo gbòó, n óo tọ̀ọ́ láyé,ati pé inú ilé mi ni n óo sì kú sí.
19 Mo ta gbòǹgbò lọ síbi omi,ìrì sì ń sẹ̀ sí ẹ̀ka mi ní alaalẹ́.
20 Ọlá hàn lára mi,agbára mi sì ń di titun nígbà gbogbo.
21 Àwọn eniyan á dákẹ́ jẹ́ẹ́, wọn á farabalẹ̀ gbọ́ tèmi,wọ́n sì ń gba ìmọ̀ràn mi pẹlu.