1 Nígbà tí ó yá, Jobu bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, ó fi ọjọ́ ìbí ara rẹ̀ bú.
2 Ó ní:
3 “Ègún ni fún ọjọ́ tí wọ́n bí mi,ati alẹ́ tí wọ́n lóyún mi.
4 Jẹ́ kí ọjọ́ náà ṣókùnkùn biribiri!Kí Ọlọrun má ṣe ka ọjọ́ náà sí,kí ìmọ́lẹ̀ má ṣe tàn sí i mọ́.