10 nítorí pé kò sé inú ìyá minígbà tí ó fẹ́ bí mi,bẹ́ẹ̀ ni kò sì mú ibi kúrò lọ́nà mi.
11 “Kí ló dé tí n kò kúnígbà tí ìyá mi ń rọbí lọ́wọ́, tí ó fẹ́ bí mi,tabi kí n kú, lẹsẹkẹsẹ tí wọ́n bí mi?
12 Kí ló dé tí ìyá mi gbé mi lẹ́sẹ̀?Kí ló dé tí ó fi fún mi lọ́mú?
13 Ǹ bá ti dùbúlẹ̀,ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́;ǹ bá ti sùn,ǹ bá sì ti máa sinmi
14 pẹlu àwọn ọba ati àwọn ìgbìmọ̀ àgbáyé, tí wọ́n ti sùn,àwọn tí wọ́n tún àlàpà kọ́ fún ara wọn;
15 tabi pẹlu àwọn ọmọ aládé tí wọ́n ní wúrà,tí fadaka sì kún ilé wọn.
16 Tabi kí n rí bí ọmọtí a bí ní ọjọ́ àìpé,tí a bò mọ́lẹ̀ láì tíì lajú sáyé.