2 Ó ní:
3 “Ègún ni fún ọjọ́ tí wọ́n bí mi,ati alẹ́ tí wọ́n lóyún mi.
4 Jẹ́ kí ọjọ́ náà ṣókùnkùn biribiri!Kí Ọlọrun má ṣe ka ọjọ́ náà sí,kí ìmọ́lẹ̀ má ṣe tàn sí i mọ́.
5 Ṣe é ní ọjọ́ ìṣúdudu,ati òkùnkùn biribiri.Kí ìkùukùu ṣíji bò ó,kí òkùnkùn sì dẹ́rù bà á.
6 Kí òkùnkùn ṣú bo alẹ́ ọjọ́ náà biribiri,kí á yọ ọ́ kúrò ninu àwọn ọjọ́tí ó wà ninu ọdún,kí á má sì ṣe kà á kúnàwọn ọjọ́ tí wọ́n wà ninu oṣù.
7 Kí alẹ́ ọjọ́ náà di òfo,kí á má ṣe gbọ́ ìró ayọ̀ ninu rẹ̀ mọ́.
8 Kí àwọn tí wọ́n ń fi ọjọ́ gégùn-ún fi gégùn-ún,àní àwọn tí wọ́n lè fi àṣẹ rú Lefiatani sókè.