16 “Bí mo bá fi ohunkohun pọ́n talaka lójú rí,tabi kí n fi opó sílẹ̀ ninu àìní,
17 tabi kí n dá oúnjẹ mi jẹ,láìfún ọmọ aláìníbaba jẹ
18 (láti ìgbà èwe rẹ̀ ni mo ti ń ṣe bíi baba fún un,tí mo sì ń tọ́jú rẹ̀ láti inú ìyá rẹ̀);
19 bí mo bá ti rí ẹni tí ó ń kú lọ,nítorí àìrí aṣọ bora,tabi talaka tí kò rí ẹ̀wù wọ̀,
20 kí ó sì súre fún mi,nítorí pé ara rẹ̀ móorupẹlu aṣọ tí a fi irun aguntan mi hun,
21 bí mo bá fi ìyà jẹ aláìníbaba,nítorí pé mo mọ eniyan ní ilé ẹjọ́,
22 jẹ́ kí apá mi já kúrò léjìká mi,kí ó yọ ní oríkèé rẹ̀.