20 kí ó sì súre fún mi,nítorí pé ara rẹ̀ móorupẹlu aṣọ tí a fi irun aguntan mi hun,
21 bí mo bá fi ìyà jẹ aláìníbaba,nítorí pé mo mọ eniyan ní ilé ẹjọ́,
22 jẹ́ kí apá mi já kúrò léjìká mi,kí ó yọ ní oríkèé rẹ̀.
23 Nítorí ẹ̀rù ìpọ́njú láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun ń bà mí,nítorí ògo rẹ̀, n kò lè dán irú rẹ̀ wò.
24 “Bí mo bá gbójú lé wúrà,tí mo sì fi ojúlówó wúrà ṣe igbẹkẹle mi,
25 bí mo bá ń yọ̀ nítorí pé mo ní ọrọ̀ pupọ,tabi nítorí pé ọwọ́ mi ti ba ọpọlọpọ ohun ìní.
26 Tí mo bá ti wo oòrùn nígbà tí ó ń ràn,tabi tí mo wo òṣùpá ninu ẹwà rẹ̀: