7 Bí mo bá ti yí ẹsẹ̀ kúrò ní ọ̀nà tààrà,tí mò ń ṣe ojúkòkòrò,tí ọwọ́ mi kò sì mọ́,
8 jẹ́ kí ẹlòmíràn kórè oko mi,kí o sì fa ohun ọ̀gbìn mi tu.
9 “Bí ọkàn mi bá fà sí obinrin olobinrin,tabi kí n máa pẹ́ kọ̀rọ̀ lẹ́nu ọ̀nà aládùúgbò mi;
10 jẹ́ kí iyawo mi máa se oúnjẹ fún ẹlòmíràn,kí ẹlòmíràn sì máa bá a lòpọ̀.
11 Nítorí ó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó burú jù,ẹ̀ṣẹ̀ tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún.
12 Iná ajónirun ni,tí yóo run gbogbo ohun ìní mi kanlẹ̀.
13 “Bí mo bá kọ̀ láti fetí sí ẹjọ́ àwọniranṣẹkunrin ati iranṣẹbinrin mi,nígbà tí wọ́n bá fẹ̀sùn kàn mí,