14 Bí Ọlọrun bá gba ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,tí ó sì gba èémí rẹ̀ pada sọ́dọ̀,
15 gbogbo eniyan ni yóo ṣègbé,tí wọn yóo sì pada di erùpẹ̀.
16 “Bí ẹ bá ní òye, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ.
17 Ǹjẹ́ ẹni tí ó kórìíra ìdájọ́ ẹ̀tọ́ lè jẹ́ olórí?Àbí ẹ lè dá olódodo ati alágbára lẹ́bi?
18 Ẹni tí ó tó pe ọba ní eniyan lásán,tí ó tó pe ìjòyè ní ẹni ibi;
19 ẹni tí kì í ṣe ojuṣaaju fún àwọn ìjòyè,tí kì í sì í ka ọlọ́rọ̀ sí ju talaka lọ,nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn.
20 Wọn á kú ikú òjijì, ní ọ̀gànjọ́ òru;á mi gbogbo eniyan jìgìjìgì, wọn a sì kú.Ikú á mú àwọn alágbára lọ láì jẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn wọ́n.