2 “Ẹ gbọ́rọ̀ mi, ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n,ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ẹ ní ìmọ̀,
3 nítorí bí ahọ́n ti í máa ń tọ́ oúnjẹ wò,bẹ́ẹ̀ ni etí náà lè máa tọ́ ọ̀rọ̀ wò
4 Ẹ jẹ́ kí á yan ohun tí ó tọ́,kí á jọ jíròrò ohun tí ó dára láàrin ara wa.
5 Jobu sọ pé òun kò jẹ̀bi,ó ní Ọlọrun ni ó kọ̀ tí kò dá òun láre.
6 Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun jàre, Ọlọrun ka òun kún òpùrọ́,bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò dẹ́ṣẹ̀, ọgbẹ́ òun kò ṣe é wòsàn.
7 “Ta ló dàbí Jobu,tí ń kẹ́gàn Ọlọrun nígbà gbogbo,
8 tí ó ń bá àwọn aṣebi kẹ́gbẹ́,tí ó sì ń bá àwọn eniyan burúkú rìn?