5 Gbójú sókè kí o wo ojú ọ̀run,ati àwọn ìkùukùu tí ó wà lókè.
6 Bí o bá dẹ́ṣẹ̀, kò ṣe Ọlọrun ní àìrójú,bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bá pọ̀, kò jámọ́ nǹkankan fún un.
7 Bí o bá jẹ́ olódodo,kí ni ó dà fún Ọlọrun,tabi kí ni ó ń rí gbà lọ́wọ́ rẹ?
8 Àwọn eniyan burúkú bíì rẹ, ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ lè pa lára,àwọn ọmọ eniyan ni òdodo rẹ sì lè jẹ́ anfaani fún.
9 “Àwọn eniyan ń kígbe nítorí ọpọlọpọ ìnira,wọ́n ń bẹ̀bẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́,nítorí àwọn alágbára ń tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó bèèrè pé,‘Níbo ni Ọlọrun Ẹlẹ́dàá mi wà,tíí fún ni ní orin ayọ̀ lóru,
11 ẹni tí ó ń kọ́ wa lẹ́kọ̀ọ́ ju àwọn ẹranko lọ,Ó sì fún wa ní ọgbọ́n ju àwọn ẹyẹ lọ?’