1 “Nígbà tí mo gbọ́, ọkàn mi wárìrì,ó sì fò sókè ní ipò rẹ̀.
2 Gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ń dún bí ààrá,ati ariwo tí ń ti ẹnu rẹ̀ jáde.
3 Ó rán mànàmáná rẹ̀ sí wọn jákèjádò ojú ọ̀run,títí dé òpin ilẹ̀ ayé.
4 Lẹ́yìn náà, a gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,ó sọ̀rọ̀ ninu ọlá ńlá rẹ̀,bí ìgbà tí ààrá bá sán,sibẹsibẹ kò dá mànàmáná dúróbí àwọn eniyan ti ń gbóhùn rẹ̀.
5 Ohùn Ọlọrun dún bí ààrá tìyanu-tìyanu,a kò lè rí ìdí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
6 Ó pàṣẹ pé kí yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀,bẹ́ẹ̀ náà ni òjò wẹliwẹli,ati ọ̀wààrà òjò.
7 Ó ká gbogbo eniyan lọ́wọ́ iṣẹ́ kò,kí wọ́n lè mọ iṣẹ́ rẹ̀.