10 tí mo sì pa ààlà fún un,tí mo sé ìlẹ̀kùn mọ́ ọn,
11 tí mo wí pé, ‘Dúró níhìn-ín, o kò gbọdọ̀ kọjá ibẹ̀,ibí ni ìgbì líle rẹ ti gbọdọ̀ dáwọ́ dúró?’
12 Jobu, láti ọjọ́ tí o ti dé ayé,ǹjẹ́ o ti pàṣẹ pé kí ilẹ̀ mọ́ rí,tabi pé kí àfẹ̀mọ́jú mọ́ àkókò rẹ̀,
13 kí ìmọ́lẹ̀ lè tàn sí gbogbo ayé,kí ó sì lè gbọn àwọn ẹni ibi dànù,kúrò ní ibi ìsápamọ́sí wọn?
14 A ti yí ayé pada bí amọ̀ tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀,ati bí aṣọ tí a pa láró.
15 A mú ìmọ́lẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹni ibi,a sì ká wọn lápá kò.
16 “Ṣé o ti wọ orísun òkun lọ rí,tabi o ti rìn nísàlẹ̀ ibú rí?