12 Jobu, láti ọjọ́ tí o ti dé ayé,ǹjẹ́ o ti pàṣẹ pé kí ilẹ̀ mọ́ rí,tabi pé kí àfẹ̀mọ́jú mọ́ àkókò rẹ̀,
13 kí ìmọ́lẹ̀ lè tàn sí gbogbo ayé,kí ó sì lè gbọn àwọn ẹni ibi dànù,kúrò ní ibi ìsápamọ́sí wọn?
14 A ti yí ayé pada bí amọ̀ tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀,ati bí aṣọ tí a pa láró.
15 A mú ìmọ́lẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹni ibi,a sì ká wọn lápá kò.
16 “Ṣé o ti wọ orísun òkun lọ rí,tabi o ti rìn nísàlẹ̀ ibú rí?
17 Ṣé a ti fi ìlẹ̀kùn ikú hàn ọ́ rí,tabi o ti rí ìlẹ̀kùn òkùnkùn biribiri rí?
18 Ṣé o mọ̀ bí ayé ti tóbi tó?Dá mi lóhùn, bí o bá mọ àwọn nǹkan wọnyi.