18 Ṣé o mọ̀ bí ayé ti tóbi tó?Dá mi lóhùn, bí o bá mọ àwọn nǹkan wọnyi.
19 “Níbo ni ọ̀nà ilé ìmọ́lẹ̀,ibo sì ni ibùgbé òkùnkùn,
20 tí o óo fi lè mú un lọ sí ààyè rẹ̀,tí o fi lè mọ ọ̀nà tí ó lọ sí ilé rẹ̀?
21 Dájúdájú o mọ̀, nítorí pé wọ́n ti bí ọ nígbà náà,o sá ti dàgbà!
22 “Ṣé o ti wọ àwọn ilé ìkẹ́rùsí, tí mò ń kó yìnyín pamọ́ sí rí,tabi ibi tí mò ń kó òjò dídì sí,
23 àní, àwọn tí mo ti pamọ́ de àkókò ìyọnu,fún ọjọ́ ogun ati ọjọ́ ìjà?
24 Ṣé o mọ ibi tí ìmọ́lẹ̀ ti ń tàn wá,tabi ibi tí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ti ń fẹ́ wá sórí ayé?